KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | TA NI ÀWỌN ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ?
Kí Ni Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Gbà Gbọ́?
Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà gbọ́ pé “Gbogbo Ìwé Mímọ́ ni Ọlọ́run mí sí.” (2 Tímótì 3:16) À ń lo Bíbélì láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa Ẹlẹ́dàá, ìlànà inú rẹ̀ sì ń jẹ́ kí ìgbésí ayé wa nítumọ̀.
Bíbélì sọ pé: “Kí àwọn ènìyàn lè mọ̀ pé ìwọ, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jèhófà, ìwọ nìkan ṣoṣo ni Ẹni Gíga Jù Lọ lórí gbogbo ilẹ̀ ayé.” (Sáàmù 83:18) Torí náà, Jèhófà Ọlọ́run nìkan là ń jọ́sìn. À sì ń sọ orúkọ rẹ̀ di mímọ̀ fáwọn èèyàn torí pé a jẹ́ Ẹlẹ́rìí rẹ̀.
Níwọ̀n bá a ti jẹ́ Kristẹni, a gbà gbọ́ pé Jésù “Ọmọ Ọlọ́run” * wá sí ayé, ó sì di Mèsáyà. (Jòhánù 1:
“Tí wọ́n bá ka Bíbélì, wọ́n gbà pé Ọlọ́run ló ń bá àwọn sọ̀rọ̀. Tí wọ́n bá ní ìṣòro kan, wọ́n á ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kí wọ́n lè mọ bí wọ́n á ṣe yanjú ìṣòro náà. . . . Wọ́n gbà pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run yè.”
Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà gbà gbọ́ pé bí àwọn ìlànà Bíbélì ṣe ṣàwọn èèyàn láǹfààní láyé àtijọ́, bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe lè ṣe wá láǹfààní lóde òní. (Aísáyà 48:
^ ìpínrọ̀ 5 Bíbélì tún sọ pé Jésù ni “Ọmọ bíbí kan ṣoṣo ti Ọlọ́run,” torí pé òun ni ẹni àkọ́kọ́ tí Jèhófà fúnra rẹ̀ dá.