Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Olùkọ́ Ńlá Náà
Inú Bíbélì ni ìmọ̀ràn tó dáa jù láyé wà. Àwọn ọmọ á kọ́ ohun tí Bàbá wọn ọ̀run sọ, kì í ṣe ohun tí èèyàn lásán sọ.
Ohun Tó Yẹ Kí Àwọn Òbí Ṣe fún Àwọn Ọmọ Wọn
Bí a ṣe ṣe ìwé yìí á jẹ́ kí àwọn ọmọdé sọ ohun tó wà lọ́kàn wọn lórí àwọn kókó pàtàkì kan fún àwọn tó ń ka ìwé náà fún wọn.
ORÍ 1
Ohun Tó Mú Kí Jésù Jẹ́ Olùkọ́ Ńlá
Irú àwọn nǹkan wo ni Jésù fi kọ́ni? Ibo sì ni ohun tó fi kọ́ni ti wá?
ORÍ 2
Lẹ́tà Kan Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Tó Fẹ́ràn Wa
Inú ìwé kan tó ṣeyebíye ju gbogbo ìwé lọ ni lẹ́tà yìí wà.
ORÍ 3
Ẹni Tí Ó Dá Ohun Gbogbo
Ta ló dá àwọn ẹyẹ, tó sì kọ́ wọn bí wọ́n ṣe ń kọrin? Tá ló dá àwọn koríko? Tá ló dá ẹ?
ORÍ 4
Ọlọ́run Ní Orúkọ Kan
Gbogbo wa la ní orúkọ. Ṣé o mọ orúkọ Ọlọ́run? Kí ló dé tí orúkọ rẹ̀ fi ṣe pàtàkì?
ORÍ 6
Olùkọ́ Ńlá Náà Sin Àwọn Ẹlòmíràn
Ṣé inú rẹ máa ń dùn tí àwọn èèyàn bá ṣe ohun tó dáa sí ẹ? Inú gbogbo wa ló máa ń dùn, Olùkọ́ Ńlá náà sì mọ̀ bẹ́ẹ̀.
ORÍ 7
Ìgbọràn Ń Dáàbò Bò Ọ́
Àwọn ọmọdé lè kẹ́kọ̀ọ́ lọ́dọ̀ àwọn àgbà. Tí Ọlọ́run bá sọ pé ká ṣe ohun kan, kó dá wa lójú pé ohun tó dáa jù nìyẹn.
ORÍ 10
Agbára Jésù Ju Ti Àwọn Ẹ̀mí Èṣù Lọ
Kò yẹ ká máa bẹ̀rù àwọn ẹ̀mí èṣù, àmọ́ ó yẹ ká ṣọ́ra kí wọ́n má bàa ṣì wá lọ́nà.
ORÍ 11
Ìrànlọ́wọ́ Látọ̀dọ̀ Àwọn Áńgẹ́lì Ọlọ́run
Àwọn áńgẹ́lì Jèhófà máa ń ran àwọn tó nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ tí wọ́n sì ń sìn ín lọ́wọ́.
ORÍ 20
Ǹjẹ́ O Máa Ń Fẹ́ Jẹ́ Ẹni Àkọ́kọ́ Nígbà Gbogbo?
Kí ni Jésù sọ fún àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ nígbà tí wọ́n ń jiyàn lórí ọ̀rọ̀ yìí?
ORÍ 25
Ǹjẹ́ Àwọn Tó Ń Ṣe Ohun Búburú Lè Yí Padà?
Àpẹẹrẹ Sọ́ọ̀lù àti ti aṣẹ́wó kan jẹ́ ká mọ ìdáhùn.
ORÍ 26
Ìdí Tó Fi Nira Láti Máa Ṣe Rere
Kí ni àwọn èèyàn burúkú ṣe máa ṣe tó ò bá ṣe ohun tí wọ́n sọ?
ORÍ 27
Ta Ni Ọlọ́run Rẹ?
Oríṣiríṣi ọlọ́run ni àwọn èèyàn máa ń sìn. Kí ló yẹ kó o ṣe? Àwọn ọ̀dọ́ Hébérù mẹ́ta jẹ́ ká mọ ìdáhùn.
ORÍ 28
Bí A Ṣe Lè Mọ Ẹni Tó Yẹ Kí Á Ṣègbọràn Sí
“Ẹ san àwọn ohun ti Késárì padà fún Késárì, ṣùgbọ́n àwọn ohun ti Ọlọ́run fún Ọlọ́run.”
ORÍ 29
Ǹjẹ́ Gbogbo Àpèjẹ Ni Inú Ọlọ́run Dùn Sí?
Ṣé o mọ̀ pé Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa àwọn àpèjẹ mélòó kan? A lè mọ ojú tí Ọlọ́run fi wò wọ́n.
ORÍ 30
Ìrànlọ́wọ́ Láti Borí Ìbẹ̀rù
Olùkọ́ Ńlá náà ò sọ pé ó máa rọrùn láti sin Jèhófà, àmọ́ ohun tá a lè ṣe wà ká lè ní ìgboyà, ká sì rí ìrànwọ́.
ORÍ 32
Bí Ọlọ́run Ṣe Dáàbò Bo Jésù
Kọ́ nípa bí Jèhófà ṣe dáàbò bo àwọn tó fẹ́ pa Jésù nígbà tó wà ní ọmọdé.
ORÍ 35
A Lè Jí Dìde Kúrò Nínú Ikú!
Ọlọ́run fún Jésù lágbára láti jí àwọn èèyàn dìde, títí kan àwọn ọmọdé.
ORÍ 37
Bí A Ṣe Lè Rántí Jèhófà àti Ọmọ Rẹ̀
Jésù kọ́ àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ní ọ̀nà pàtàkì kan tí wọ́n lè gbà máa rántí ohun tí Jèhófà àti Jésù ṣe fún wa.
ORÍ 40
Bí A Ṣe Lè Mú Inú Ọlọ́run Dùn
Òwe inú Bíbélì kan sọ pé: “Ọmọ mi, jẹ́ ọlọ́gbọ́n, kí o sì mú ọkàn-àyà mi yọ̀.”
ORÍ 42
Ìdí Tó Fi Yẹ Ká Máa Ṣiṣẹ́
Tí èèyàn bá ń ṣiṣẹ́, ó máa ń jẹ́ kí ara àti ọpọlọ ṣiṣẹ́ dáadáa. Kọ́ bí o ṣe lè gbádùn iṣẹ́.
ORÍ 43
Àwọn Wo Ni Arákùnrin àti Arábìnrin Wa?
Ṣé a lè ka àwọn tí kì í ṣe ọmọ ìyá, ọmọ bàbá wa mọ́ wọn?
ORÍ 44
Ó Yẹ Kí Àwọn Ọ̀rẹ́ Wa Fẹ́ràn Ọlọ́run
“Kí a má ṣì yín lọ́nà. Ẹgbẹ́ búburú a máa ba ìwà rere jẹ́.”
ORÍ 45
Kí Ni Ìjọba Ọlọ́run? Bí A Ṣe Lè Fi Hàn Pé À Ń Fẹ́ Ẹ
Nígbà tí Jésù bá bẹ̀rẹ̀ sí í darí gbogbo ohun tó wà láyé, ó máa ṣe àwọn àyípadà ńlá kan.