Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 54

“Èyí Ni Ọ̀nà”

“Èyí Ni Ọ̀nà”

(Àìsáyà 30:​20, 21)

  1. 1. Ọ̀nà kan wà tó ti

    Wà lọ́jọ́ tó ti pẹ́.

    Jésù sọ nípa rẹ̀

    Nígbà tó wá sáyé.

    Mo kẹ́kọ̀ọ́, mo sì ti

    Wá mọ ọ̀nà yìí gan-an.

    Ọ̀nà àlàáfíà yìí

    Wà nínú Bíbélì.

    (ÈGBÈ)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’

  2. 2. Ọ̀nà ìfẹ́ lo wà,

    Má ṣe wọ̀tún-wòsì.

    Bíbélì fi hàn pé

    Jèhófà jẹ́ ìfẹ́.

    Ìfẹ́ tó dára, tó

    Jinlẹ̀ ló ní sí wa.

    Ọ̀nà tí à ń sọ yìí

    Kan ìgbé ayé wa.

    (Ègbè)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’

  3. 3. Ọ̀nà ìyè la wà,

    Má ṣe bojú wẹ̀yìn.

    Kò sí ibòmíràn

    Tá a lè lọ, tá a lè rí

    Àlàáfíà àtìfẹ́

    Tí Jáà ṣèlérí rẹ̀.

    Ọ̀nà ìyè nìyí,

    Ọpẹ́ yẹ Jèhófà.

    (Ègbè)

    Ọ̀nà ìyè àìnípẹ̀kun nìyí.

    Tẹsẹ̀ mọ́rìn, má ṣe wọ̀tún-wòsì!

    Jèhófà ń sọ pé: ‘Má yà kúrò;

    Má ṣe wẹ̀yìn, ojú ọ̀nà lo wà.’