Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Orin 141

À Ń Wá Àwọn Ọ̀rẹ́ Àlàáfíà

À Ń Wá Àwọn Ọ̀rẹ́ Àlàáfíà

Wà á jáde:

(Lúùkù 10:6)

  1. Jésù pàṣẹ pé: ‘Ẹ wàásù òótọ́.’

    Lójò lẹ́ẹ̀rùn, níbi gbogbo,

    Ó ń sọ̀rọ̀ Jáà fáwọn èèyàn.

    Jésù nífẹ̀ẹ́ àgùntàn Ọlọ́run.

    Ó ń wá wọn lọ

    ní òwúrọ̀ títí ’lẹ̀ fi ṣú.

    Nílé délé, lópòópónà,

    À ń wàásù fún gbogbo èèyàn

    Pé láìpẹ́ gbogbo

    ìṣòro yóò dópin.

    (ÈGBÈ)

    Kárí ayé

    À ń wá àwọn ọ̀rẹ́ àlàáfíà,

    Ó yẹ ká rí

    Àwọn èèyàn tó fẹ́ rí’gbàlà,

    Ká sì rí i pé

    A sapá wa.

  2. Àkókò ń lọ, ká tẹra mọ́ṣẹ́ yìí.

    Ọ̀pọ̀ èèyàn, ọ̀pọ̀ ẹ̀mí,

    Là ń sapá láti gbà là.

    Ìfẹ́ ló ń mú ká ṣáà máa wá wọn lọ.

    À ń wo ọgbẹ́ ọkàn wọn sàn,

    à ń táyé wọn ṣe.

    Nílùú délùú, lópòópónà,

    Tá a bá rẹ́ni tó gbọ́rọ̀ wa,

    Ayọ̀ tó ń fún wa ń mú ká máa báṣẹ́ lọ.

    (ÈGBÈ)

    Kárí ayé

    À ń wá àwọn ọ̀rẹ́ àlàáfíà,

    Ó yẹ ká rí

    Àwọn èèyàn tó fẹ́ rí’gbàlà,

    Ká sì rí i pé

    A sapá wa.