Sáàmù 104:1-35

  • Yin Ọlọ́run torí àwọn ohun àgbàyanu tó wà nínú ìṣẹ̀dá

    • Ayé máa wà títí láé (5)

    • Oúnjẹ àti wáìnì wà fún ẹni kíkú (15)

    • “Àwọn iṣẹ́ rẹ mà pọ̀ o!” (24)

    • ‘Tí a bá mú ẹ̀mí kúrò, wọ́n á kú’ (29)

104  Jẹ́ kí n* yin Jèhófà.+ Ìwọ Jèhófà Ọlọ́run mi, o tóbi gan-an.+ O fi ògo* àti ọlá ńlá wọ ara rẹ láṣọ.+   O fi ìmọ́lẹ̀+ bora bí aṣọ;O na ọ̀run bí aṣọ àgọ́.+   Ó tẹ́ igi àjà àwọn yàrá òkè rẹ̀ sínú omi lókè,*+Ó fi àwọsánmà ṣe kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ̀,+Ó ń lọ lórí ìyẹ́ apá ẹ̀fúùfù.+   Ó dá àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ ní ẹ̀mí,Ó dá àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀ ní iná tó ń jó nǹkan run.+   Ó ti gbé ayé kalẹ̀ sórí ìpìlẹ̀ rẹ̀;+A kì yóò ṣí i nípò* títí láé àti láéláé.+   O fi ibú omi bò ó bí aṣọ.+ Omi náà bo àwọn òkè.   Bí wọ́n ṣe gbọ́ ìbáwí rẹ, wọ́n fẹsẹ̀ fẹ;+Bí wọ́n ṣe gbọ́ ìró ààrá rẹ, ìbẹ̀rù mú kí wọ́n sá lọ   —Àwọn òkè lọ sókè,+ àwọn àfonífojì sì lọ sílẹ̀—Sí ibi tí o ṣe fún wọn.   O pa ààlà tí wọn ò gbọ́dọ̀ kọjá,+Kí wọ́n má bàa bo ayé mọ́. 10  Ó ń mú kí omi sun jáde ní àwọn àfonífojì;Wọ́n ń ṣàn gba àárín àwọn òkè. 11  Wọ́n ń pèsè omi fún gbogbo ẹran inú igbó;Àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó ń fi wọ́n pa òùngbẹ. 12  Orí àwọn igi tó wà létí wọn ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ń wọ̀ sí;Wọ́n ń kọrin láàárín àwọn ẹ̀ka tó léwé dáadáa. 13  Ó ń bomi rin àwọn òkè láti àwọn yàrá òkè rẹ̀.+ Iṣẹ́ ọwọ́* rẹ ń tẹ́ ilẹ̀ ayé lọ́rùn.+ 14  Ó ń mú kí koríko hù fún àwọn ẹran orí pápá láti jẹÀti ewéko fún ìlò aráyé,+Kí oúnjẹ lè jáde látinú ilẹ̀ 15  Àti wáìnì tó ń mú ọkàn èèyàn yọ̀,+Òróró tó ń mú kí ojú dánÀti oúnjẹ tó ń gbé ẹ̀mí ẹni kíkú ró.+ 16  Àwọn igi Jèhófà rí omi mu,Àwọn igi kédárì Lẹ́bánónì tó gbìn, 17  Ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ ń kọ́ ìtẹ́ sí. Ilé ẹyẹ àkọ̀+ wà lórí àwọn igi júnípà. 18  Àwọn òkè gíga wà fún àwọn ewúrẹ́ orí òkè;+Àwọn àpáta gàǹgà jẹ́ ibi ààbò fún àwọn gara orí àpáta.+ 19  Ó dá òṣùpá láti máa sàmì àkókò;Oòrùn mọ ìgbà tó yẹ kó wọ̀.+ 20  O mú kí òkùnkùn ṣú, alẹ́ sì lẹ́,+Gbogbo ẹranko inú igbó sì ń jẹ̀ kiri. 21  Àwọn ọmọ kìnnìún* ń ké ramúramù nítorí ẹran tí wọ́n fẹ́ pa jẹ,+Wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn lọ́dọ̀ Ọlọ́run.+ 22  Nígbà tí oòrùn bá yọ,Wọ́n á pa dà, wọ́n á sì lọ dùbúlẹ̀ sínú ihò wọn. 23  Èèyàn á lọ sẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀,Á sì ṣiṣẹ́ títí di àṣálẹ́. 24  Àwọn iṣẹ́ rẹ mà pọ̀ o, Jèhófà!+ Gbogbo wọn lo fi ọgbọ́n ṣe.+ Ayé kún fún àwọn ohun tí o ṣe. 25  Ibẹ̀ ni òkun wà, ó tóbi, ó sì fẹ̀,Àìmọye ohun alààyè ló wà nínú rẹ̀, èyí tó kéré àti èyí tó tóbi.+ 26  Ibẹ̀ ni àwọn ọkọ̀ òkun ti ń rìnÀti Léfíátánì,*+ tí o dá kí ó lè máa ṣeré nínú rẹ̀. 27  Gbogbo wọn ń dúró dè ọ́Kí o lè fún wọn ní oúnjẹ lásìkò.+ 28  Ohun tí o fún wọn ni wọ́n ń kó jọ.+ Tí o bá ṣí ọwọ́ rẹ, wọ́n á ní ọ̀pọ̀ ohun rere ní ànító.+ 29  Tí o bá gbé ojú rẹ pa mọ́, ìdààmú á bá wọn. Tí o bá mú ẹ̀mí wọn kúrò, wọ́n á kú, wọ́n á sì pa dà sí erùpẹ̀.+ 30  Tí o bá rán ẹ̀mí rẹ jáde, a ó dá wọn,+Ìwọ á sì sọ ojú ilẹ̀ di ọ̀tun. 31  Ògo Jèhófà yóò wà títí láé. Jèhófà yóò máa yọ̀ lórí àwọn iṣẹ́ rẹ̀.+ 32  Ó wo ayé, ayé sì mì tìtì;Ó fọwọ́ kan àwọn òkè, wọ́n sì rú èéfín.+ 33  Màá kọrin sí Jèhófà+ jálẹ̀ ayé mi;Màá kọ orin ìyìn* sí Ọlọ́run mi ní gbogbo ìgbà tí mo bá fi wà láàyè.+ 34  Kí èrò mi dùn mọ́ ọn.* Èmi yóò máa yọ̀ nínú Jèhófà. 35  Àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò pa rẹ́ kúrò láyé,Àwọn ẹni burúkú kò sì ní sí mọ́.+ Jẹ́ kí n* yin Jèhófà. Ẹ yin Jáà!*

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “iyì.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Ní Héb., “sínú omi.”
Tàbí “mú kí ó ta gbọ̀n-ọ́n gbọ̀n-ọ́n.”
Tàbí “Èso iṣẹ́.”
Tàbí “ọmọ kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe (onígọ̀gọ̀).”
Tàbí “kọrin.”
Tàbí kó jẹ́, “Kí ohun tí mò ń rò nípa rẹ̀ dùn mọ́ni.”
Tàbí “ọkàn mi.”
Tàbí “Halelúyà!” “Jáà” ni ìkékúrú Jèhófà.