Sáàmù 142:1-7

  • Àdúrà ìdáǹdè kúrò lọ́wọ́ àwọn tó ń ṣe inúnibíni

    • “Kò síbi tí mo lè sá lọ” (4)

    • ‘Ìwọ ni gbogbo ohun tí mo ní’ (5)

Másíkílì.* Ti Dáfídì, nígbà tó wà nínú ihò àpáta.+ Àdúrà. 142  Mo fi ohùn mi ké pe Jèhófà fún ìrànlọ́wọ́;+Mo fi ohùn mi bẹ Jèhófà pé kó ṣojú rere sí mi.  Mo tú ẹ̀dùn ọkàn mi jáde níwájú rẹ̀;Mo sọ nípa wàhálà mi níwájú rẹ̀+  Nígbà tí àárẹ̀ mú ẹ̀mí mi.* Ò ń ṣọ́ ọ̀nà mi.+ Wọ́n dẹ pańpẹ́ pa mọ́ dè míNí ọ̀nà tí mò ń rìn.  Wo ọwọ́ ọ̀tún mi, kí o sì rí iPé kò sẹ́ni tó rí tèmi rò.*+ Kò síbi tí mo lè sá lọ;+Kò sẹ́ni tí ọ̀rọ̀ mi* ká lára.  Jèhófà, mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́. Mo sọ pé: “Ìwọ ni ibi ààbò mi,+Gbogbo ohun tí mo ní* lórí ilẹ̀ alààyè.”  Fetí sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,Nítorí wọ́n ti bá mi kanlẹ̀. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn tó ń ṣe inúnibíni sí mi,+Torí wọ́n lágbára jù mí lọ.  Mú mi* jáde kúrò nínú àjà ilẹ̀Kí n lè máa yin orúkọ rẹ. Kí àwọn olódodo yí mi ká,Nítorí o ti ṣemí lóore.

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “tí mi ò lágbára mọ́.”
Ní Héb., “tó dá mi mọ̀.”
Tàbí “ọ̀rọ̀ ọkàn mi.”
Ní Héb., “Ìpín mi.”
Tàbí “ọkàn mi.”