Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

Màá Wá Ìṣúra

Màá Wá Ìṣúra

Wà á jáde:

  1. 1. Bí mò ń kẹ́kọ̀ọ́, Ọ̀r’Ọlọ́run

    Ìṣura wà tí mò ń rí

    Mò ń ṣèwádìí, kẹ́kọ̀ọ́ jinlẹ̀

    Fún ìṣẹ́jú mélòó kan

    Àfi bíi pé èmi alára wà níbẹ̀

    Ó ń jẹ́ kí n lóye ohun tí Bíbélì sọ

    (ÈGBÈ)

    Wòó bíi póo wà ńbẹ̀, kóo sì ṣàṣàrò,

    Ló ń jẹ́ n lóye ohun tó ṣẹlẹ̀.

    Àti bí mo ṣe lè ṣohun tó tọ́,

    Kí n sì tún ní ìwà rere;

    Kí n ní ìwà rere.

  2. 2. Ronú nípa àwọn èèyàn;

    Tó dára, tí kò dára.

    Àpẹẹrẹ wọn ń jẹ́ kí n lóye

    Bí Ọlọ́run ṣe ń ronú.

    Nígbà míì àṣàrò mi máa ń jẹ́ kí n lè mọ

    Bí mo ṣe lè wá túbọ̀ máa wu Jèhófà.

    (ÈGBÈ)

    Wòó bíi póo wà ńbẹ̀, kóo sì ṣàṣàrò,

    A ó wá lóye nǹkan tó ṣẹlẹ̀.

    Àti bí a ṣe lè ṣohun tó tọ́,

    Ká sì tún ní ìwà rere;

    Ká ní ìwà rere

    (ÈGBÈ)

    Wòó bíi póo wà ńbẹ̀, kóo sì ṣàṣàrò,

    Wòó bíi póo wà ńbẹ̀, kóo sì ṣàṣàrò,

    Wòó bíi póo wà ńbẹ̀, kóo sì ṣàṣàrò.