Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ PÉ

Kí Ni Mo Lè Ṣe Káwọn Òbí Mi Má Bàa Máa Tojú Bọ Ọ̀rọ̀ Mi Jù?

Kí Ni Mo Lè Ṣe Káwọn Òbí Mi Má Bàa Máa Tojú Bọ Ọ̀rọ̀ Mi Jù?

 Kí ló lè mú káwọn òbí ẹ máa yọjú sọ́rọ̀ ẹ?

 Ire ẹ làwọn òbí ẹ rò pé àwọn ń wá. Àmọ́ lójú tìẹ, ṣe ni wọ́n ń tojú bọ ọ̀rọ̀ ẹ. Bí àpẹẹrẹ:

  •   Ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Erin sọ pé: “Dádì mi á mú fóònù mi, wọ́n á ní kí n ṣí i, wọ́n á wá máa wo gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo fi ránṣẹ́ sáwọn èèyàn àtàwọn tí wọ́n fi ráńṣẹ́ sí mi. Tí mi ò bá jẹ́ kí wọ́n ṣe é, wọ́n á máa rò pé nǹkan kan wà tí mò ń fi pa mọ́.”

  •   Denise, tó ti lé lọ́mọ ogún [20] ọdún báyìí, rántí bí mọ́mì ẹ̀ ṣe máa ń yẹ àwọn tó fi fóònù ẹ̀ pè wò. Ó ní, “Wọ́n á máa wo àwọn nọ́ńbà tí mo pè níkọ̀ọ̀kan, wọ́n á béèrè ẹni tó ni ín, wọ́n á sì máa bi mí lóhun tí mo bá wọn sọ.”

  •   Ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Kayla sọ pé mọ́mì òun lọ ka ìwé kan tóun máa ń kọ ọ̀rọ̀ ara òun sí. Ó ní, “Gbogbo nǹkan tó bá ń ṣe mí ni mo máa ń kọ síbẹ̀, kódà, mo kọ àwọn nǹkan nípa mọ́mì fúnra wọn sínú ìwé yẹn! Àtìgbà yẹn ni mi ò ti kọ ọ̀rọ̀ ara mi sínú ìwé kankan mọ́.”

 Òótọ́ ibẹ̀ ni pé: Ojúṣe àwọn òbí ẹ ni láti bójú tó ẹ, ìwọ kọ́ lo sì máa kọ́ wọn bí wọ́n á ṣe ṣe é. Ó lè fẹ́ dà bíi pé wọ́n ń tojú bọ ọ̀rọ̀ ẹ nígbà míì. Àmọ́ fọkàn balẹ̀, àwọn ohun kan wà tó o lè ṣe kó má bàa máa ṣe ẹ́ bí i pé wọ́n ń tojú bọ ọ̀rọ̀ ẹ.

 Ohun tó o lè ṣe

 Má fi nǹkan kan pa mọ́. Bíbélì rọ̀ wá pé ká “máa jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo.” (Hébérù 13:18, Bíbélì Mímọ́) Gbìyànjú láti máa sọ òótọ́ fáwọn òbí ẹ. Tó o bá ń sọ òótọ́, tó ò sì fi ohunkóhun pa mọ́ fún wọn, ó ṣeé ṣe kí wọ́n má yọjú sọ́rọ̀ ẹ mọ́ bíi ti tẹ́lẹ̀.

 Rò ó wò ná: Ṣé àwọn òbí ẹ fọkàn tán ẹ? Tí wọ́n bá ní aago báyìí ni kó o délé, ṣé ìgbà yẹn náà lo máa ń délé? Ṣé o kì í fi àwọn ọ̀rẹ́ tó o ní pa mọ́? Ṣé o kì í fi àwọn ohun tó ò ń ṣe pa mọ́?

“Àfi kí n gba ohun táwọn òbí mi bá sọ. Mi ò kí ń fọ̀rọ̀ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ sí mi pa mọ́ fún wọn. Ohunkóhun tí wọ́n bá bi mí ni mo máa ń sọ fún wọn, ìyẹn ti wá mú kí wọ́n fọkàn tán mi, wọn kì í sì í wá kúlẹ̀kúlẹ̀ gbogbo ohun tí mò ń ṣe mọ́.”​—Delia.

 Ní sùúrù. Bíbélì sọ pé: “Ẹ máa wádìí ohun tí ẹ̀yin fúnra yín jẹ́.” (2 Kọ́ríńtì 13:5) Ó lè pẹ́ díẹ̀ kí àwọn òbí ẹ tó lè fọkàn tán ẹ, àmọ́ ó tó bẹ́ẹ̀ ó jù bẹ́ẹ̀ lọ.

 Rò ó wò ná: Àwọn òbí ẹ ti jẹ́ ọ̀dọ́ rí. Kí lo rò pé ìyẹn ní ín ṣe pẹ̀lú bí ọ̀rọ̀ ẹ ṣe máa ń jẹ wọ́n lógún?

 “Ó dà bíi pé àwọn òbí máa ń rántí àwọn àṣìṣe tí wọ́n ṣe nígbà tí wọ́n wà lọ́dọ̀ọ́, wọn kì í sì í fẹ́ káwọn ọmọ wọn tún ṣe irú ẹ̀.”​—Daniel.

 Máa fọ̀rọ̀ ro ara ẹ wò. Máa fira ẹ sí ipò àwọn òbí ẹ. Bíbélì sọ pé ìyàwó tó dáńgájíá máa ń “ṣọ́ àwọn ohun tí ń lọ nínú agbo ilé rẹ̀”, bàbá rere sì máa ń fi “ìbáwí àti ìlànà èrò orí Jèhófà” tọ́ àwọn ọmọ rẹ̀. (Òwe 31:27; Éfésù 6:4) Torí náà, kò sí ọgbọ́n tó o fẹ́ dá sí i táwọn òbí ẹ ò fi ní máa dá sí ọ̀rọ̀ ayé ẹ.

 Rò ó wò ná: Ká sọ pé òbí ni ẹ́, tó o sì ti mọ bẹ́yin ọ̀dọ́ ṣe máa ń ṣe, ṣé o kàn máa fi ọmọ ẹ sílẹ̀, kó máa ṣe nǹkan tó wù ú láìbi í ní ohunkóhun?

“Téèyàn bá wà lọ́dọ̀ọ́, ó lè fẹ́ dà bíi pé àwọn òbí ń ‘tojú bọ’ ọ̀rọ̀ èèyàn. Àmọ́ ní báyìí tí mo ti dàgbà, ó ti wá yé mi ìdí tó fi yẹ káwọn òbí ṣe bẹ́ẹ̀. Torí pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ wa ni.”​—James.