Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ PÉ

Kí Ni Mo Lè Ṣe Tí Kò Fi Ní Máa Rẹ̀ Mí Jù?

Kí Ni Mo Lè Ṣe Tí Kò Fi Ní Máa Rẹ̀ Mí Jù?

 Tó bá jẹ́ pé ó sábà máa ń rẹ̀ ẹ́ gan-an, àpilẹ̀kọ yìí máa ràn ẹ́ lọ́wọ́.

 Kí ló máa ń fà á

  •   Mo fẹ́ ṣe tibí, mo fẹ́ ṣe tọ̀hún. Obìnrin kan tó ń jẹ́ Julie sọ pé: “Wọ́n máa ń sọ pé ká máa ṣe dáadáa ní gbogbo apá ìgbésí ayé wa, ká máa sunwọ̀n sí i, wọ́n tún ní ká ní àfojúsùn tó nítumọ̀, ká sì lé wọn bá. Nǹkan kì í rọrùn fún wa rárá nítorí bí wọ́n ṣe ń fúngun mọ́ wa yìí!”

  •   Ìmọ̀ ẹ̀rọ. Fóònù àtàwọn ẹ̀rọ ìgbàlódé tá à ń lò ti mú kó rọrùn láti mọ nǹkan tó ń lọ lórí ìkànnì, èyí lè mú kọ́wọ́ wa dí nígbà gbogbo, ó sì lè mú kó rẹ̀ wá gan-an.

  •   Oorun. Ọ̀dọ́bìnrin kan tó ń jẹ́ Miranda sọ pé: “Ilé ìwé, iṣẹ́ àti eré ìnàjú ni kì í jẹ́ káwọn míì tètè sùn, wọ́n sì máa ń tètè jí, bó ṣe máa ń rí fún wọn nìyẹn lọ́pọ̀ ìgbà torí kò sóun tí wọ́n lè ṣe sí i.” Irú nǹkan báyìí lè jẹ́ kó rẹni gan-an.

 Ìdí tó fi yẹ kó o mọ̀

 Bíbélì gbóríyìn fún àwọn tó ń ṣiṣẹ́ kára. (Òwe 6:​6-8; Róòmù 12:11) Àmọ́ kò fẹ́ ká máa ṣiṣẹ́ bí aago, tó fi jẹ́ pé a ò ní ráyè bójú tó ìlera wa àtàwọn nǹkan míì tó ṣe pàtàkì.

 “Ṣàdédé ni mo rántí pé mi ò tíì jẹun látàárọ̀, ìdí sì ni pé ọwọ́ mi dí gan-an. Mo ti wá rí i báyìí pé tí wọ́n bá ní kí n ṣe iṣẹ́ kan tí mo mọ̀ pé ó máa pa mí lára, ó máa dáa tí mo bá sọ pé mi ò ní lè ṣe é.”​—Ashley.

 Ó ní ìdí tí Bíbélì fi sọ pé: “Ààyè ajá sàn ju òkú kìnnìún lọ.” (Oníwàásù 9:4) Tó o bá ń lo ara ẹ lálòjù ó lè dà bíi pé o lágbára bíi kìnnìún. Àmọ́ tó o bá ń jẹ́ kó rẹ̀ ẹ́ jù, ó léwu fún ìlera ẹ.

 Ohun tó o lè ṣe

  •   Sọ pé oò ní lè ṣe é. Bíbélì sọ pé: “Ọgbọ́n wà pẹ̀lú àwọn amẹ̀tọ́mọ̀wà.” (Òwe 11:2) Ẹni tó bá mẹ̀tọ́mọ̀wà máa ń mọ ibi tágbára ẹ̀ mọ, kò sì ní máa ṣe nǹkan tó ju agbára ẹ̀ lọ.

     “Ẹni tó sábà máa ń rẹ̀ jù ni ẹni tó máa ń ṣòro fún láti sọ pé mi ò lè ṣe é, tó jẹ́ pé gbogbo nǹkan ní wọ́n máa ń fẹ́ dáwọ́ lé. Irú ẹni bẹ́ẹ̀ ò mọ̀wọ̀n ara rẹ̀. Bópẹ́ bóyá ó máa rẹ̀ ẹ́ gan-an.”​—Jordan.

  •   Máa sùn dáadáa. Bíbélì sọ pé: “Ẹ̀kúnwọ́ kan ìsinmi sàn ju ẹ̀kúnwọ́ méjì iṣẹ́ àṣekára àti lílépa ẹ̀fúùfù.” (Oníwàásù 4:6) Oorun ni wọ́n ń pè ní “oúnjẹ ọpọlọ,” àmọ́ ọ̀pọ̀ àwọn ọ̀dọ́ ni kì í sùn tó wákàtí mẹ́jọ sí mẹ́wàá, iye wákàtí tó sì yẹ kí wọ́n máa fi sùn nìyẹn.

     “Tí mo bá ní nǹkan púpọ̀ láti ṣe, mi ò kì í ráyè sùn dáadáa. Àmọ́ lọ́jọ́ tí mo bá sùn dáadáa, màá lókun láti ṣiṣẹ́, inú mi sì máa dùn gan-an lọ́jọ́ kejì.”​—Brooklyn.

  •   Ṣètò ara rẹ. Bíbélì sọ pé: “Dájúdájú, àwọn ìwéwèé ẹni aláápọn máa ń yọrí sí àǹfààní.” (Òwe 21:5) Tó o bá kọ́ bó o ṣe lè máa ṣètò ara rẹ pẹ̀lú àkókò rẹ, ó máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ tó o bá dàgbà.

     “Tó ò bá fẹ́ máa fún ara rẹ ní wàhálà jù, á dáa kó o ṣètò àwọn nǹkan tó o fẹ́ ṣe lọ́jọ́ kọ̀ọ̀kan. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, wàá mọ àwọn apá ibi tó yẹ kó o ṣe àtúnṣe sí kó o má bàa rẹ̀ ẹ́ jù.”​—Vanessa